Ìwé Òwe 22:20-24 BIBELI MIMỌ (BM)

20. Ṣebí mo ti kọ ọgbọ̀n àkọsílẹ̀ fún ọ lórí ìmọ̀ràn ati ọgbọ́n,

21. láti fi ohun tí ó tọ̀nà tí ó sì jẹ́ òtítọ́ hàn ọ́,kí o lè fi ìdáhùn pípé fún ẹni tí ó rán ọ.

22. Má ja talaka lólè, nítorí pé ó jẹ́ talaka,má sì dájọ́ èké fún ẹni tí ara ń ni.

23. Nítorí OLUWA yóo gbèjà wọn,yóo fìyà jẹ àwọn tí wọn ń jẹ wọ́n níyà.

24. Má bá oníbìínú eniyan kẹ́gbẹ́,má sì bá onínúfùfù da nǹkan pọ̀.

Ìwé Òwe 22