Ìwé Òwe 16:9-19 BIBELI MIMỌ (BM)

9. Eniyan lè jókòó kí ó ṣètò ìgbésẹ̀ rẹ̀,ṣugbọn OLUWA níí tọ́ ìṣísẹ̀ ẹni.

10. Pẹlu ìmísí Ọlọrun ni ọba fi ń sọ̀rọ̀,ìdájọ́ aiṣododo kò gbọdọ̀ ti ẹnu rẹ̀ jáde.

11. Ti OLUWA ni òṣùnwọ̀n pípé,iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀ ni gbogbo ohun tí à ń wọ̀n.

12. Àwọn ọba kórìíra ibi ṣíṣe,nítorí nípa òdodo ni a fìdí ìjọba múlẹ̀.

13. Inú ọba a máa dùn sí olódodo,ọba sì máa ń fẹ́ràn àwọn tí ń sọ òtítọ́.

14. Iranṣẹ ikú ni ibinu ọba,ọlọ́gbọ́n eniyan níí tù ú lójú.

15. Ìyè wà ninu ojurere ọba,ojurere rẹ̀ sì dàbí ṣíṣú òjò ní àkókò òjò àkọ́rọ̀.

16. Ó sàn kí eniyan ní òye ju kí ó ní wúrà lọ,ó sì sàn kí eniyan yan ìmọ̀ ju kí ó yan fadaka lọ.

17. Olóòótọ́ kì í tọ ọ̀nà ibi,ẹni tí ń ṣọ́ra, ẹ̀mí ara rẹ̀ ni ó ń pamọ́.

18. Ìgbéraga ní ń ṣáájú ìparun,agídí ní ń ṣáájú ìṣubú.

19. Ó sàn kí eniyan jẹ́ onírẹ̀lẹ̀ pẹlu àwọn talakaju kí ó bá agbéraga pín ìkógun lọ.

Ìwé Òwe 16