Ìwé Òwe 15:27-30 BIBELI MIMỌ (BM)

27. Àwọn tí ń ṣojúkòkòrò èrè àìtọ́ ń kó ìyọnu bá ilé wọn,ṣugbọn àwọn tí wọn kórìíra àbẹ̀tẹ́lẹ̀ yóo yè.

28. Olódodo a máa ronú kí ó tó fèsì ọ̀rọ̀,ṣugbọn ọ̀rọ̀ burúkú níí máa jáde lẹ́nu àwọn eniyan burúkú.

29. OLUWA jìnnà sí eniyan burúkú,ṣugbọn a máa gbọ́ adura olódodo.

30. Ọ̀yàyà a máa mú inú dùn,ìròyìn ayọ̀ a sì máa mú ara yá.

Ìwé Òwe 15