Ìwé Òwe 15:21-30 BIBELI MIMỌ (BM)

21. Ayọ̀ ni ìwà òmùgọ̀ jẹ́ fún aláìgbọ́n,ṣugbọn ẹni tí ó ní òye a máa rìn ní ọ̀nà ẹ̀tọ́.

22. Àìsí ìmọ̀ràn a máa mú kí ètò dàrú,ṣugbọn ọpọlọpọ ìmọ̀ràn a máa mú kí ó yọrí sí rere.

23. Ìdáhùn kíkún a máa fúnni láyọ̀,kí ọ̀rọ̀ bọ́ sí àsìkò dára lọpọlọpọ!

24. Ọ̀nà ọlọ́gbọ́n lọ tààrà sinu ìyè,kí ó má baà bọ́ sinu isà òkú.

25. OLUWA a máa wó ilé agbéraga,ṣugbọn ó ṣe àmójútó ààlà opó.

26. Ohun ìríra ni èrò ọkàn ẹni ibi lójú OLUWA,ṣugbọn ọrọ̀ àwọn ẹni mímọ́ jẹ́ dídùn inú rẹ̀.

27. Àwọn tí ń ṣojúkòkòrò èrè àìtọ́ ń kó ìyọnu bá ilé wọn,ṣugbọn àwọn tí wọn kórìíra àbẹ̀tẹ́lẹ̀ yóo yè.

28. Olódodo a máa ronú kí ó tó fèsì ọ̀rọ̀,ṣugbọn ọ̀rọ̀ burúkú níí máa jáde lẹ́nu àwọn eniyan burúkú.

29. OLUWA jìnnà sí eniyan burúkú,ṣugbọn a máa gbọ́ adura olódodo.

30. Ọ̀yàyà a máa mú inú dùn,ìròyìn ayọ̀ a sì máa mú ara yá.

Ìwé Òwe 15