Ìwé Òwe 12:10-18 BIBELI MIMỌ (BM)

10. Olódodo a máa ka ẹ̀mí ẹran ọ̀sìn rẹ̀ sí,ṣugbọn eniyan burúkú rorò sí tirẹ̀.

11. Ẹni tí ó bá ń dáko yóo ní ọ̀pọ̀ oúnjẹ,ṣugbọn ẹni tí ó bá ń lo àkókò rẹ̀ lórí ohun tí kò lérè, kò lọ́gbọ́n lórí.

12. Ilé ìṣọ́ àwọn eniyan burúkú yóo di òkítì àlàpà,ṣugbọn gbòǹgbò eniyan rere a máa fìdí múlẹ̀ sí i.

13. Ọ̀rọ̀ ẹnu eniyan burúkú a máa mú un bíi tàkúté,ṣugbọn olódodo a máa bọ́ ninu ìyọnu.

14. Ọ̀rọ̀ ẹnu ọlọ́gbọ́n a máa mú ìtẹ́lọ́rùn bá a,a sì máa jèrè iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀.

15. Ọ̀nà òmùgọ̀ níí dára lójú tirẹ̀,ṣugbọn ọlọ́gbọ́n a máa fetí sí ìmọ̀ràn.

16. Bí inú bá ń bí òmùgọ̀, kíá ni gbogbo eniyan yóo mọ̀,ṣugbọn ọlọ́gbọ́n kìí ka ọ̀rọ̀ àbùkù sí.

17. Ẹni tí ó bá ń sọ òtítọ́ a máa jẹ́rìí òdodo,ṣugbọn irọ́ ni ẹlẹ́rìí èké máa ń pa.

18. Ẹni tí í bá máa ń sọ̀rọ̀ jàbùjàbù láìronú,ọ̀rọ̀ rẹ̀ dàbí kí á fi idà gún eniyan,ṣugbọn ọ̀rọ̀ ọlọ́gbọ́n dàbí ẹni wo ọgbẹ́ sàn.

Ìwé Òwe 12