Ìwé Òwe 11:6-10 BIBELI MIMỌ (BM)

6. Ìwà òdodo àwọn olóòótọ́ yóo gbà wọ́n,ṣugbọn ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ àwọn ọ̀dàlẹ̀ yóo dè wọ́n nígbèkùn.

7. Nígbà tí àwọn eniyan burúkú bá kú,ìrètí wọn yóo di asán,bẹ́ẹ̀ ni ìrètí àwọn tí kò mọ Ọlọrun yóo di òfo.

8. OLUWA a máa gba olódodo lọ́wọ́ ìyọnu,ṣugbọn ẹni ibi a bọ́ sinu wahala.

9. Ẹni tí kò mọ Ọlọrun a máafi ẹnu ba ti aládùúgbò rẹ̀ jẹ́,ṣugbọn nípa ìmọ̀ a máa gba olódodo sílẹ̀.

10. Nígbà tí nǹkan bá ń dára fún olódodo,gbogbo ará ìlú a máa yọ̀,nígbà tí eniyan burúkú bá kú,gbogbo ará ìlú a sì hó ìhó ayọ̀.

Ìwé Òwe 11