Ìwé Òwe 11:16-24 BIBELI MIMỌ (BM)

16. Obinrin onínúrere gbayì,ṣugbọn ọrọ̀ nìkan ni ìkà yóo ní.

17. Ẹni tí ó ṣoore ṣe é fún ara rẹ̀,ẹni tí ó sì ń ṣìkà ó ń ṣe é fún ara rẹ̀.

18. Owó ọ̀yà èké ni eniyan burúkú óo gbà,ṣugbọn ẹni tí ó bá hùwà òdodo yóo gba èrè òtítọ́.

19. Ẹni tí ó dúró ṣinṣin lórí òdodo yóo yè,ṣugbọn ẹni tí ó bá ń lépa ibi yóo kú.

20. Ẹni ìríra ni àwọn alágàbàgebè lójú OLUWA,ṣugbọn àwọn tí ọ̀nà wọn mọ́ ni ìdùnnú fún un.

21. Dájúdájú ẹni ibi kò ní lọ láìjìyà,ṣugbọn a óo gba àwọn olódodo là.

22. Bí òrùka wúrà ní imú ẹlẹ́dẹ̀ni obinrin tí ó lẹ́wà tí kò ní làákàyè.

23. Ìfẹ́ ọkàn olódodo a máa yọrí sí rere,ṣugbọn ìrètí eniyan burúkú a máa já sí ibinu.

24. Ẹnìkan wà tíí máa ṣe ìtọrẹ àánú káàkiri,sibẹsibẹ àníkún ni ó ń ní,ẹnìkan sì wà tí ó háwọ́,sibẹsibẹ aláìní ni.

Ìwé Òwe 11