Ìwé Òwe 10:4-10 BIBELI MIMỌ (BM)

4. Ìmẹ́lẹ́ máa ń fa òṣì,ṣugbọn ẹni tí ó bá tẹpá mọ́ṣẹ́ yóo di ọlọ́rọ̀.

5. Ọlọ́gbọ́n ní ọmọ tí ó kórè ní àkókò ìkórè,ṣugbọn ọmọ tí ó bá ń sùn lákòókò ìkórèa máa kó ìtìjú báni.

6. Ibukun wà lórí olódodo,ṣugbọn eniyan burúkú a máa fi ìwà ìkà sinu,a sì máa sọ̀rọ̀ rere jáde lẹ́nu.

7. Ayọ̀ ni ìrántí olódodo,ṣugbọn orúkọ eniyan burúkú yóo di ohun ìgbàgbé.

8. Ọlọ́gbọ́n a máa pa òfin mọ́,ṣugbọn òmùgọ̀ onísọkúsọ yóo di ẹni ìparun.

9. Ẹni tí ó bá jẹ́ olóòótọ́ eniyan, yóo máa rìn láìfòyà,ṣugbọn àṣírí alágàbàgebè yóo tú.

10. Ẹni tí bá ń ṣẹ́jú sí ni láti sọ̀rọ̀ èké, a máa dá ìjàngbọ̀n sílẹ̀,ṣugbọn ẹni tí bá ń báni wí ní gbangba, ń wá alaafia.

Ìwé Òwe 10