31. Ìwà tí ẹ̀gbọ́n rẹ hù ni ìwọ náà ń hù, nítorí náà, ìyà tí mo fi jẹ ẹ̀gbọ́n rẹ ni n óo fi jẹ ìwọ náà.”
32. OLUWA Ọlọrun ní:“ọpọlọpọ ìyà tí mo fi jẹ ẹ̀gbọ́n rẹ ni n óo fi jẹ ọ́,wọn óo fi ọ́ rẹ́rìn-ín,wọn óo sì fi ọ́ ṣẹ̀sín,nítorí ìyà náà óo pọ̀.
33. Ìyà óo jẹ ọ́ lọpọlọpọ,ìbànújẹ́ óo sì dé bá ọ.N óo mú ìpayà ati ìsọdahoro bá ọ,bí mo ṣe mú un bá Samaria, ẹ̀gbọ́n rẹ.