Diutaronomi 28:15-18 BIBELI MIMỌ (BM)

15. “Ṣugbọn bí o kò bá gbọ́ ti OLUWA Ọlọrun rẹ, tí o kò sì pa àwọn òfin ati ìlànà rẹ̀ mọ́, bí mo ti fi lélẹ̀ fún ọ lónìí, gbogbo àwọn ègún wọnyi ni yóo ṣẹ sí orí rẹ tí yóo sì mọ́ ọ.

16. “Ègún ni fún ọ ní ààrin ìlú, ègún ni fún ọ ní oko.

17. “Ègún ni fún ọkà rẹ ati oúnjẹ rẹ.

18. “Ègún ni fún ọmọ inú rẹ, ati fún èso ilẹ̀ rẹ ati fún àwọn ọmọ mààlúù rẹ ati àwọn ọmọ aguntan rẹ.

Diutaronomi 28