Àwọn Adájọ́ 5:20-23 BIBELI MIMỌ (BM)

20. Láti ojú ọ̀run ni àwọn ìràwọ̀ ti ń jagun,àní láti ààyè wọn lójú ọ̀nà wọn,ni wọ́n ti bá Sisera jà.

21. Odò Kiṣoni kó wọn lọ,odò Kiṣoni, tí ó kún àkúnya.Máa yan lọ, ìwọ ọkàn mi, máa fi agbára yan lọ.

22. Àwọn ẹṣin sáré dé, pẹlu ariwo pátákò ẹsẹ̀ wọn,wọ́n bẹ̀rẹ̀ sí fi ẹsẹ̀ kilẹ̀.”

23. Angẹli OLUWA ní, “Ìlú ègún ni ìlú Merosi,ẹni ègún burúkú sì ni àwọn olùgbé rẹ̀,nítorí pé wọ́n kọ̀, wọn kò wá ran OLUWA lọ́wọ́;wọn kò ran OLUWA lọ́wọ́ láti gbógun ti àwọn alágbára.”

Àwọn Adájọ́ 5