10. Ṣé bíríkì ni wọ́n fi kọ́ àwọn ilé tí ó wó lulẹ̀?Òkúta gbígbẹ́ ni a óo fi tún wọn kọ́.Igi sikamore ni a fi kọ́ èyí tí wọ́n dà wó,ṣugbọn igi kedari dáradára ni a óo lò dípò wọn.
11. Nítorí náà OLUWA ti gbé ọ̀tá dìde sí wọn:Ó ti rú àwọn ọ̀tá wọn sókè sí wọn:
12. Àwọn ará Siria láti ìhà ìlà oòrùn,ati àwọn ará Filistia láti ìhà ìwọ̀ oòrùn;wọn óo gbé Israẹli mì.Sibẹsibẹ inú OLUWA kò rọ̀,bẹ́ẹ̀ ni kò dá ọwọ́ ìjà rẹ̀ dúró.
13. Sibẹsibẹ àwọn ọmọ Israẹli kò pada sí ọ̀dọ̀ ẹni tí ó jẹ wọ́n níyà,bẹ́ẹ̀ ni wọn kò wá OLUWA àwọn ọmọ-ogun.
14. Nítorí náà, OLUWA yóo fi ìyà jẹ Israẹli.Ní ọjọ́ kan ṣoṣo, yóo gé Israẹli lórí ati nírù.
15. Àwọn àgbààgbà ati àwọn ọlọ́lá wọn ni orí,àwọn wolii tí ń kọ́ àwọn eniyan ní ẹ̀kọ́ èké sì ni ìrù
16. Àwọn tí ń darí àwọn eniyan wọnyi ń ṣì wọ́n lọ́nà ni,àwọn tí wọn ń tọ́ sọ́nà sì ń já sinu ìparun.