Aisaya 59:8-12 BIBELI MIMỌ (BM)

8. Ẹ kò mọ ọ̀nà alaafia,kò sí ìdájọ́ òdodo ní ọ̀nà yín.Ẹ ti mú kí ọ̀nà yín wọ́,ẹni tó bá ba yín rìn kò ní ní alaafia.

9. Àwọn eniyan bá dáhùn pé,“Nítorí náà ni ìdájọ́ òtítọ́ fi jìnnà sí wa,tí òdodo kò sì fi dé ọ̀dọ̀ wà.Ìmọ́lẹ̀ ni à ń retí, ṣugbọn òkùnkùn ló ṣú,ìtànṣán oòrùn ni à ń retí, ṣugbọn ìkùukùu ni ó bolẹ̀.

10. À ń táràrà lára ògiri bí afọ́jú,à ń táràrà bí ẹni tí kò lójú.À ń kọsẹ̀ lọ́sàn-án gangan,bí ẹni tí ó jáde ní àfẹ̀mọ́júmọ́a dàbí òkú láàrin àwọn alágbára.

11. Gbogbo wa ń bú bí ẹranko beari,a sì ń ké igbe ẹ̀dùn bí àdàbà.À ń retí ìdájọ́ òdodo, ṣugbọn kò sí;à ń retí ìgbàlà, ṣugbọn ó jìnnà sí wa.

12. “Nítorí àìdára wa pọ̀ níwájú rẹ,ẹ̀ṣẹ̀ wa sì ń jẹ́rìí lòdì sí wa;nítorí àwọn àìdára wa wà pẹlu wa,a sì mọ àwọn ẹ̀ṣẹ̀ wa:

Aisaya 59