Aisaya 52:7-13 BIBELI MIMỌ (BM)

7. Ẹsẹ̀ ẹni tí ń mú ìyìn rere bọ̀ ti dára tó lórí òkè,ẹni tí ń kéde alaafia,tí ń mú ìyìn rere bọ̀,tí sì ń kéde ìgbàlà,tí ń wí fún Sioni pé,“Ọlọrun rẹ jọba.”

8. Gbọ́, àwọn aṣọ́de rẹ gbóhùn sókè,gbogbo wọn jọ ń kọrin ayọ̀,nítorí wọ́n jọ fi ojú ara wọn rí i,tí OLUWA pada dé sí Sioni.

9. Ẹ jọ máa kọrin pọ̀,gbogbo ilẹ̀ Jerusalẹmu tí a sọ di aṣálẹ̀,nítorí OLUWA yóo tu àwọn eniyan rẹ̀ ninu,yóo ra Jerusalẹmu pada.

10. OLUWA yóo lo agbára mímọ́ rẹ̀, lójú àwọn orílẹ̀-èdè,gbogbo eniyan, títí dé òpin ayé, yóo sì rí ìgbàlà Ọlọrun wa.

11. Ẹ jáde, ẹ jáde ẹ kúrò níbẹ̀,ẹ má fọwọ́ kan ohun àìmọ́ kan,ẹ jáde kúrò láàrin rẹ̀, kí ẹ sì wẹ ara yín mọ́,ẹ̀yin tí ẹ̀ ń gbé ohun èlò OLUWA.

12. Nítorí pé ẹ kò ní fi ìkánjú jáde,bẹ́ẹ̀ ni ẹ kò ní sáré jáde.Nítorí OLUWA yóo máa lọ níwájú yín,Ọlọrun Israẹli yóo sì wà lẹ́yìn yín.

13. Wò ó! Iranṣẹ mi yóo ṣe àṣeyọría óo gbé e ga, a óo gbé e lékè;yóo sì di ẹni gíga,

Aisaya 52