Aisaya 49:1-4 BIBELI MIMỌ (BM)

1. Ẹ gbọ́, ẹ̀yin ilẹ̀ etí òkun.Ẹ fetí sílẹ̀ sí ọ̀rọ̀ mi, ẹ̀yin ará ilẹ̀ òkèèrè,láti inú oyún ni OLUWA ti pè mí,láti inú ìyá mi wá ni ó ti dárúkọ mi.

2. Ó ṣe ẹnu mi bí idà mímú,ó fi mí pamọ́ sí ibi òjìji ọwọ́ rẹ̀,ó ṣe mí ní ọfà tí ó mú,ó fi mí pamọ́ sinu apó rẹ̀.

3. Ó sọ fún mi pé, “Iranṣẹ mi ni ọ́, ìwọ Israẹli,àwọn eniyan óo máa yìn mí lógo nítorí rẹ.”

4. Ṣugbọn mo dáhùn pé,“Mo ti ṣiṣẹ́ àṣedànù.Mo ti lo agbára mi ṣòfò, mo ti fi ṣe àṣedànù,sibẹsibẹ ẹ̀tọ́ mi ń bẹ lọ́dọ̀ OLUWA.”Ẹ̀san mi ń bẹ lọ́dọ̀ Ọlọrun mi, yóo san án fún mi.

Aisaya 49