Aisaya 41:3-10 BIBELI MIMỌ (BM)

3. A máa lépa wọn, a sì máa kọjá wọn láìléwu,ní ọ̀nà tí ẹsẹ̀ rẹ̀ kò tẹ̀ rí.

4. Ta ló ṣe èyí?Iṣẹ́ ọwọ́ ta sì ni?Tí ó pe ìran dé ìran láti ìbẹ̀rẹ̀?Èmi OLUWA ni, ẹni àkọ́kọ́ ati ẹni ìkẹyìn.

5. “Àwọn erékùṣù rí i, ẹ̀rù bà wọ́n,gbogbo òpin ayé gbọ̀n rìrì wọ́n ti súnmọ́ tòsí, wọ́n ti dé.

6. Olukuluku ń ran ẹnìkejì rẹ̀ lọ́wọ́,ó ń sọ fún arakunrin rẹ̀ pé, ‘Ṣara gírí.’

7. Agbẹ́gilére ń gba alágbẹ̀dẹ wúrà níyànjúẹni tí ń fi òòlù lu irin ń kí ẹni tí ń dán irin tí wọ́n ti rọ,Ó ń wí pé: ‘Òjé tí a fi jó o dára.’Wọ́n kàn án ní ìṣó,ó le dáradára, kò le mì.

8. “Ìwọ ní tìrẹ, Israẹli iranṣẹ mi,Jakọbu, ìwọ tí mo ti yàn,ọmọ bíbí inú Abrahamu, ọ̀rẹ́ mi.

9. Ìwọ tí mo mú wá láti òpin ayé,tí mo pè láti ìkangun ayé tí ó jìnnà jùlọ,mo wí fún ọ pé, ‘Iranṣẹ mi ni ọ́,mo ti yàn ọ́, n kò ní ta ọ́ nù.’

10. Má bẹ̀rù, nítorí mo wà pẹlu rẹ,má fòyà, nítorí èmi ni Ọlọrun rẹ.N óo fún ọ ní agbára, n óo sì ràn ọ́ lọ́wọ́;ọwọ́ ọ̀tún mi, ọwọ́ ìṣẹ́gun, ni n óo fi gbé ọ ró.

Aisaya 41