1. Ó sì ṣe ní ọdún kẹrin Dáríúsì ọba, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ́ Sekaráyà wá ni ọjọ́ kẹrin oṣù Kísíléfì tí ń se oṣù kẹsàn-án.
2. Nígbà tí wọ́n rán Sérésérì àti Régémélékì, àti àwọn ènìyàn wọn sí ilé Ọlọ́run láti wá ojú rere Olúwa.
3. Àti láti bá àwọn àlùfáà tí ó wà ní ilé Olúwa àwọn ọmọ-ogun, àti àwọn wòlíì sọ̀rọ̀ wí pé, “Ṣé kí èmi ó sọkún ní oṣù kárùnún kí èmi ya ara mi sọ́tọ̀, bí mo ti ń ṣe láti ọdún mélòó wọ̀nyí wá bí?”
4. Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa àwọn ọmọ-ogun tọ̀ mí wá pé,