Sekaráyà 4:10-14 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

10. “Ṣùgbọ́n ta ni ha kẹ́gàn ọjọ́ ohun kékeré? Nítorí wọn ó yọ̀ ní, ìwọ̀n lọ́wọ́ Serubábélì.“(Àwọn méje wọ̀nyí ni àwọn ojú Olúwa, tí ó ń sáré síhìn ín sọ́hùn ún ní gbogbo ayé.)”

11. Mo sì béèrè, mo sì sọ fún un pé, “Kí ni àwọn igi ólífì méjì wọ̀nyí jásí, tí ó wà ní apá ọ̀tún fìtílà àti ní apá òsì rẹ̀?”

12. Mo sì tún dáhùn, mo sì sọ fún un pé, “Kí ni àwọn ẹ̀ka méjì igi wọ̀nyí jásí, tí ń tú òróró wúrà jáde nínú ara wọn láti ẹnu ọ̀pá oníhò wúrà méjì.”

13. Ó sì dáhùn, ó wí fún mi pé, “Ìwọ kò mọ ohun tí àwọn wọ̀nyí jásí?”Mo sì wí pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́, Olúwa à mi.”

14. Ó sì wí pé, “Àwọn méjì wọ̀nyí ni àwọn tí a fi òróró yàn, tí ó dúró ti Olúwa gbogbo ayé.”

Sekaráyà 4