28. Ó jẹ́ kí wọn jáde ní ibùdó wọn,yíká àgọ́ wọn.
29. Wọn jẹ, wọ́n sí yó jọjọnítorí ó ti fún wọn ní ohun tí wọn fìtara bẹ̀bẹ̀ fún
30. Ṣùgbọ́n wọn kò kúrò nínú oúnjẹ tí wọ́n fìtara bẹ̀bẹ̀ fún,nígbà tí oúnjẹ wọn sì wà ní ẹnu wọn,
31. Ìbínú Ọlọ́run dìde sí wọnó pa àwọn tí ó jùlọ nínú wọn,ó sì lu àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin Ísírẹ́lì bolẹ̀.
32. Nínú gbogbo ìwọ̀nyí, wọn ń sá síwájú;nínú gbogbo iṣẹ́ ìyanu Rẹ̀, wọ́n kò gbàgbọ́
33. O fi òpin sí ayé wọn nínú asánàti ọdún wọn nínú ìpayà.
34. Nígbà kígbà tí Ọlọ́run bá pa wọ́n,wọn yóò wá a kirì;wọn yóò fi ìtara yípadà sí i.
35. Wọ́n rántí pé Ọlọ́run ní àpáta wọn;wí pé Ọlọ́run ọ̀gá ògo jùlọ ni olùràpadà àpáta wọn
36. Ṣùgbọ́n nígbà náà ni wọ́n yóò pọ́n-ọn pẹ̀lú ẹnu wọ́nwọ́n fí ahọ́n wọ́n purọ́ fún un;
37. Ọkàn wọn kò sòtítọ́ si i,wọn kò jẹ́ olódodo sí májẹ̀mú Rẹ̀.
38. Ṣíbẹ̀ ó ṣàánú;ó dárí àìṣedédé wọn jìnòun kò sì pa wọn runnígbà kí ì gbà ló ń dá ìbínú Rẹ̀ dúrókò sì rú ìbínú Rẹ̀ sókè
39. Ó ránti pé ẹlẹ́ran ara ni wọ́n,afẹ́fẹ́ tó ń kọjá tí kò le padà.
40. Nígbà gbogbo ní wọn ń ṣọ̀tẹ̀ síi ní ihàwọn mú-un bínú nínú ilẹ̀ tí ó di ahoro!
41. Síwájú àti síwájú wọn dán Ọlọ́run wò;wọ́n mú ẹni mímọ́ Ísírẹ́lì bínú.
42. Wọ́n kò rántí agbára Rẹ̀:ní ọjọ́ tí ó rà wọ́n padà lọ́wọ́ àwọn aninilára,
43. Ní ọjọ́ tí ó fi iṣẹ́ ìyanu Rẹ̀ hàn ní Éjíbítì,àti iṣẹ́ àmì Rẹ ni ẹkùn Sáónì