Sáàmù 68:5-10 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

5. Baba àwọn aláìní baba àti Onídàájọ́ àwọn opó ni Ọlọ́run ni ibùgbéRẹ̀ mímọ́

6. Ọlọ́run gbé ẹni òfokálẹ̀ nínú ìdílé,ó darí àwọn ẹlẹ́wọ̀n pẹ̀lú orinṣùgbọ́n àwọn ọlọ́tẹ̀ ni ń gbé nínú ilẹ̀ gbígbẹ.

7. Nígbà tí ìwọ bá jáde lónìí níwájú àwọn ènìyàn Rẹ̀, Ọlọ́run,tí ń kọjá lọ láàrin ihà, Sela

8. Ilẹ̀ mi títí,àwọn ọ̀run ń rọ òjò jáde,níwájú Ọlọ́run,ẹni Sínáì,níwájú Ọlọ́run, Ọlọ́run Ísírẹ́lì.

9. Ìwọ fún wa ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ òjò, Ọlọ́run;ìwọ tu ilé inú Rẹ̀ lára nígbà tí ó Rẹ̀ ẹ́ tan.

10. Àwọn ènìyàn Rẹ tẹ̀dó ṣíbẹ̀nínú ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìní Rẹ̀, Ọlọ́run, ìwọ pèsè fún àwọn aláìní.

Sáàmù 68