Sáàmù 35:12-18 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

12. Wọ́n fi búburú san ire fún mi;láti sọ ọkàn mi di òfo.

13. Ṣùgbọ́n bí ó ṣe ti èmi ni,nígbà tí wọn ń ṣe àìsàn,mo wọ aṣọ ọ̀fọ̀;mo fi ààwẹ̀ pọ́n ara mi lójú.Mo gba àdúrà pẹ̀lú ìtẹríbaní oókan àyà mi;

14. bí i ẹni wí pé ọ̀rẹ́ tàbí ẹ̀gbọ́nmi ní wọ́n;mo ń lọọ́ kiri bí ẹni tíń sọ̀fọ̀ fún ìyà Rẹ̀,tí o tẹríba nínú ìbànújẹ́.

15. Ṣùgbọ́n nínú ìkọ̀sẹ̀ miwọ́n kó ara wọn jọ wọ́n sì yọ̀,wọ́n kó ara wọn jọ sí mi;àní àwọn tí èmi kò mọ̀wọ́n fà mí yawọ́n kò sì dákẹ́.

16. Àwọn àgàbàgebè ń ṣe yẹ̀yẹ́mi ṣíwájú àti sí wájú síiwọ́n pa eyín wọnkeke sí mi.

17. Yóò ti pẹ́tó,ìwọ Olúwa,tí ìwọ yóò máa wò wọ́n lọ?Yọ mí kúrò nínú ìparun wọnàní ẹ̀mí i mi kúrò lọ́wọ́ kìnnìún.

18. Nígbà náà ni èmi yóò sọpẹ́ fún Ọnínú àjọ ńlá;èmi yóò máa yìn Ọ́ní àwùjọ ọ̀pọ̀ ènìyàn.

Sáàmù 35