Sáàmù 35:10-15 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

10. Gbogbo egúngún mi yóò wí pé,“ìwọ Olúwa,ta ni ó dà bí i Rẹ̀?O gba talákà làlọ́wọ́ àwọn tí ó lágbárajù wọ́n lọ,talákà àti aláìnílọ́wọ́ ẹni tí ń fi ṣe ìkógun?”

11. Àwọn ẹlẹ́rìí èké dìde;wọ́n bi mi léèrè àwọn ohuntí èmi kò mọ̀.

12. Wọ́n fi búburú san ire fún mi;láti sọ ọkàn mi di òfo.

13. Ṣùgbọ́n bí ó ṣe ti èmi ni,nígbà tí wọn ń ṣe àìsàn,mo wọ aṣọ ọ̀fọ̀;mo fi ààwẹ̀ pọ́n ara mi lójú.Mo gba àdúrà pẹ̀lú ìtẹríbaní oókan àyà mi;

14. bí i ẹni wí pé ọ̀rẹ́ tàbí ẹ̀gbọ́nmi ní wọ́n;mo ń lọọ́ kiri bí ẹni tíń sọ̀fọ̀ fún ìyà Rẹ̀,tí o tẹríba nínú ìbànújẹ́.

15. Ṣùgbọ́n nínú ìkọ̀sẹ̀ miwọ́n kó ara wọn jọ wọ́n sì yọ̀,wọ́n kó ara wọn jọ sí mi;àní àwọn tí èmi kò mọ̀wọ́n fà mí yawọ́n kò sì dákẹ́.

Sáàmù 35