Sáàmù 139:17-24 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

17. Ọlọ́run, ìrò inú Rẹ tí ṣe iyebíye tó fún mi,iye wọn ti pọ̀ tó!

18. Èmi ibá kà wọ́n, wọ́n jù iyanrin lọ ní iye:nígbà tí mo bá jí, èmi yóò wà lọ́dọ̀ Rẹ̀ ṣíbẹ̀

19. Ọlọ́run ibá jẹ pa àwọn ènìyàn búburú ní tòótọ́;nítorí náà kúrò lọ́dọ̀ mi ẹ̀yin ọkùnrin ẹ̀jẹ̀.

20. Ẹni tí ń fi inú búburú sọ̀rọ̀ sí ọ,àwọn ọ̀tá Rẹ ń pe orúkọ Rẹ ní aṣán!

21. Olúwa, ǹjẹ́ èmi kò korìíra àwọn tó korìíra Rẹ?Ǹjẹ́ inú mi kò a sì bàjẹ́ sí àwọn tí ó dìde sí ọ?

22. Èmi korìíra wọn ní àkótán;èmi kà wọ́n sí ọ̀tá mi.

23. Ọlọ́run, wádíì mi, kí ó sì mọ ọkàn mí;dán mi wò, kí ó sì mọ ìrò inú mi

24. Kí ó sì wò ó bí ipa ọ̀nà búburúkan bá wà nínú mi kí ó sìfi ẹṣẹ̀ mi lé ọ̀nà àìnípẹ̀kun.

Sáàmù 139