Sáàmù 119:16-26 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

16. Inú mi dùn sí àṣẹ Rẹ;èmi kì yóò gbàgbé ọ̀nà Rẹ.

17. Ṣe rere sí ìránṣẹ́ Rẹ, èmi yóò sì wà láàyè;èmi yóò ṣe ìgbọ́ràn sí ọ̀rọ̀ Rẹ.

18. La ojú mi kí èmi lè ríran ríohun ìyanu tí ó wà nínú òfin Rẹ.

19. Àlejò ní èmi jẹ́ láyé;Má ṣe pa àṣẹ Rẹ mọ́ fún mi.

20. Ọkàn mi pòrúúru pẹ̀lú ìfojúsọ́nànítorí òfin Rẹ nígbà gbogbo.

21. Ìwọ fi àwọn agbéraga bú, àwọn tí a fi gégùn-úntí ó sìnà kúrò nínú àṣẹ Rẹ.

22. Mú ẹ̀gàn àti àbùkù kúrò lára mi,nítorí èmi pa òfin Rẹ mọ́.

23. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn alákòóso kójọ̀pọ̀, wọ́nń sọ̀rọ̀ ìbàjẹ́ sí mi,ṣùgbọ́n ìránṣẹ́ Rẹ̀ ń ṣe àṣàrò nínú àṣẹ Rẹ.

24. Òfin Rẹ ni dídùn inú mi;àwọn ní olùbadámọ̀ràn mi.

25. Èmi tẹ̀ jẹ́ẹ́jẹ́ sínú erùpẹ̀;pa ayé mi mọ́ sí ipa ọ̀rọ̀ Rẹ.

26. Èmi tún ọ̀nà mi síròṣ ìwọ sì dá mí lóhùn;kọ́ mi ní àṣẹ Rẹ.

Sáàmù 119