Sáàmù 118:5-10 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

5. Nínú ìrora mi, mo sunkún sí Olúwa,ó sì dámi lóhùn nípa pé ó tú mi sílẹ̀.

6. Olúwa, ń bẹ fún èmi; èmi kì yóò bẹ̀rù.Kí ni ènìyàn lè ṣe si mi?

7. Olúwa n bẹ fún mi; òun ni olùrànlọ́wọ́ miNítorí náà ni èmi ó ṣe rí ìfẹ́ mi lórí àwọn ti ó kórìíra mi.

8. Ó dára láti máa gbẹ́kẹ̀lé Olúwaju àti gbẹ́kẹ̀lé ènìyàn lọ.

9. Ó dára láti máa gbẹ́kẹ̀lé Olúwaju à ti gbẹ́kẹ̀lé àwọn ọmọ aládé lọ.

10. Gbogbo àwọn orílẹ̀ èdè yí mi káàkiri,ṣùgbọ́n ní orúkọ Olúwa èmi gé wọn kúrò

Sáàmù 118