Sáàmù 118:1-8 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, nítorí tí ó dára;àánú Rẹ̀ dúró láéláé.

2. Jẹ́ kí Ísírẹ́lì wí pé:“Àánú Rẹ̀ dúró láéláé”.

3. Jẹ́ kí ilé Árónì wí pé:“Àánú Rẹ̀ dúró láéláé”.

4. Jẹ́ kí àwọn tí ó bẹ̀rù Olúwa wí pé:“Àánú Rẹ̀ dúró láéláé.”

5. Nínú ìrora mi, mo sunkún sí Olúwa,ó sì dámi lóhùn nípa pé ó tú mi sílẹ̀.

6. Olúwa, ń bẹ fún èmi; èmi kì yóò bẹ̀rù.Kí ni ènìyàn lè ṣe si mi?

7. Olúwa n bẹ fún mi; òun ni olùrànlọ́wọ́ miNítorí náà ni èmi ó ṣe rí ìfẹ́ mi lórí àwọn ti ó kórìíra mi.

8. Ó dára láti máa gbẹ́kẹ̀lé Olúwaju àti gbẹ́kẹ̀lé ènìyàn lọ.

Sáàmù 118