Sáàmù 115:14-18 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

14. Olúwa yóò mú ọ pọ̀ síi síwájú àti síwájú,ìwọ àti àwọn ọmọ Rẹ̀.

15. Ẹ fi ìbùkún fún Olúwaẹni tí ó dá ọ̀run òun ayé.

16. Ọ̀run àní ọ̀run ni ti, Olúwa:ṣùgbọ́n ayé lo fi fún ọmọ ènìyàn.

17. Òkú kò le yìn Olúwa,tàbí ẹni tí o ti lọ sí ìṣàlẹ̀ ìdákẹ́jẹ́.

18. Ṣùgbọ́n àwa o fi ìbùkún fún Olúwaláti ìsinsìn yí lọ àti títí láéláé.Ẹ yin Olúwa.

Sáàmù 115