Sáàmù 107:20-29 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

20. Ó rán ọ̀rọ̀ Rẹ̀, ara wọn sí dáó sì yọ̀ wọ́n nínú isà òkú.

21. Ẹ jẹ́ kí wọ́n fi ọpẹ́ fún Olúwa nítorí ìṣeun ìfẹ́ Rẹ̀ àti iṣẹ ìyanu Rẹ̀ fún ọmọ ènìyàn.

22. Jẹ́ kí wọn rú ẹbọ ọpẹ́kí wọn kí ó fi ayọ̀ sọ̀rọ̀ iṣẹ́ Rẹ̀.

23. Àwọn ti ń sọ̀kalẹ̀ lọ sí òkun nínú ọkọ̀ojú omi, wọn jẹ́ oníṣòwò nínú omi ńlá.

24. Wọn ri iṣẹ́ Olúwa,àti iṣẹ́ ìyanu Rẹ̀ nínú ibú

25. Nítorí tí ó pasẹ, ó sì mú ìjì fẹ́tí ó gbé ríru Rẹ̀ sókè.

26. Wọ́n gòkè lọ sí ọ̀run wọn sìtún sọ̀kalẹ̀ lọ sí ibú:nítorí ìpọ́njú ọkan wọn di omi

27. Wọ́n ń ta gbọ̀n-ọ́ngbọ̀n-ọ́n bí ọ̀mùtí ènìyàn:ọgbọ́n wọn sì dé òpin.

28. Nígbà náà wọ́n ń kígbe sókèsí Olúwa nínú ìdàámú wọn,ó sì mú wọn jáde nínú ìṣòro wọn.

29. Ó sọ ìjì di ìdákẹ́-rọ́rọ́bẹ́ẹ̀ ní rirú omi Rẹ̀ duro jẹ́ẹ́;

Sáàmù 107