Òwe 6:29-33 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

29. Bẹ́ẹ̀ ni ẹni tí ń lọ sùn pẹ̀lú aya aláya;kò sí ẹni tí ó fọwọ́ kàn án tí yóò lọ láì jìyà.

30. Àwọn ènìyàn kì í kẹ́gàn olè tí ó bá jalènítorí àti jẹun nígbà tí ebi bá ń pa á.

31. Ṣíbẹ̀ bí ọwọ́ bá tẹ̀ẹ́, ó gbọdọ̀ san ìlọ́po méjebí ó tilẹ̀ kó gbogbo ohun tó ní nílé tà.

32. Ṣùgbọ́n ẹni tí ń ṣe àgbérè kò nírònú;ẹnikẹ́ni tí ó bá ń ṣe bẹ́ẹ̀ ó ń pa ara rẹ̀ run ni

33. Ìfarapa àti ìtìjú ni tirẹ̀,ẹ̀gàn rẹ̀ kì yóò sì kúrò láéláé;

Òwe 6