Òwe 3:5-12 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

5. Gbẹ́kẹ̀lé Olúwa pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹmá ṣe sinmi lé òye ara à rẹ;

6. Jẹ́wọ́ rẹ̀ ní gbogbo ọ̀nà rẹyóò sì ṣe àkóso ọ̀nà rẹ.

7. Má ṣe jẹ́ ọlọ́gbọ́n lójú ara à rẹbẹ̀rù Olúwa kí o sì kórìíra ibi.

8. Èyí yóò mú ìlera fún ara à rẹàti okun fún àwọn egungun rẹ.

9. Fi ọrọ̀ rẹ bọ̀wọ̀ fún Olúwa,pẹ̀lú àkọ́so oko ò rẹ

10. Nígbà náà ni àká rẹ yóò kún àkúnyaàgbá rẹ yóò kún à kún wọ́ sílẹ̀ fún wáìnì tuntun.

11. Ọmọ mi, má ṣe kẹ́gàn ìbáwí Olúwamá si ṣe bínú nígbà tí ó bá ń bá ọ wí,

12. Nítorí Olúwa a máa bá àwọn tí ó fẹ́ràn wíbí baba ti í bá ọmọ tí ó bá nínú dídùn sí wí.

Òwe 3