Òwe 25:8-13 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

8. Ohun tí o ti fi ojú ara rẹ rímá ṣe kánjú gbé e lọ sílé ẹjọ́ nítorí kí ni ìwọ yóò ṣe ní ìgbẹ̀yìnbí aládùúgbò rẹ bá dójú tì ọ́?

9. Bí o bá ń ṣe àwíjàre rẹ níwájú aládùúgbò rẹ,má ṣe tú àsírí tí ẹlòmíràn ní lọ́dọ̀ rẹ,

10. àìṣe bẹ́ẹ̀ ẹni tí ó gbọ́ ọ le dójú tì ọ́orúkọ burúkú tí ìwọ bá sì gba kì yóò tán láéláé.

11. Ọ̀rọ̀ tí a sọ ní àkókò tí ó yẹó dàbí èṣo wúrà nínú àpẹẹrẹ fàdákà.

12. Bí i yẹtí wúrà tàbí ohun ọ̀ṣọ́ ti wúrà dáradárani ìbáwí ọlọ́gbọ́n fún etí tí ó bá fetísílẹ̀.

13. Bí títutù òjò yìnyín ní àsíkò ìkórèni ìránṣẹ́ tí ó jẹ́ olóòtọ́ sí àwọn tí ó rán anó ń tu ọ̀gá rẹ̀ nínú.

Òwe 25