Òwe 24:10-15 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

10. Bí ìwọ bá dákú lásìkò ìdààmúbáwo ni agbára rẹ ha ti kéré tó!

11. Gba àwọn tí a ń wọ́ lọ síbi ikú là;fa àwọn tó ń ta gbọ̀n-ọ́n gbọ̀n-ọ́n lọ síbi ìparun padà.

12. Bí ìwọ bá wí pé, “Ṣùgbọ́n a kò mọ nǹkankan nípa èyí,”ǹjẹ́ ẹni tí ń díwọ̀n ọkàn kò kíyèsíi? Ǹjẹ́ ẹni tí ń ṣọ́ ẹ̀mí rẹ kò mọ̀ ọ́?Ǹjẹ́ kò ní san án fún ẹnìkọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí ohun tí ó ti ṣe?

13. Jẹ oyin, ìwọ ọmọ mi, nítorí tí ó dára,oyin láti inú afárá oyin dùn lẹ́nu.

14. Mọ̀ pẹ̀lú pé ọgbọ́n pẹ̀lú dùn fún ọkàn rẹbí ìwọ bá rí i ìrètí ọjọ́ iwájú wà fún ọìrètí rẹ kì yóò sì já sófo.

15. Má ṣe ba ní ibùba bí i arúfin dé ilé Olódodo,má ṣe kó ibùgbé è rẹ̀ lọ;

Òwe 24