Òwe 23:16-26 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

16. Inú mi yóò sì dùn nígbà tí ètè rẹ̀ bá ń sọ̀rọ̀ títọ́.

17. Má ṣe jẹ́ kí àyà rẹ ó ṣe ìlara sí àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀,ṣùgbọ́n kí ìwọ ó wà ní ìbẹ̀rù Olúwa,ní ọjọ́ gbogbo.

18. Nítorí pé ìkẹyìn ń bẹ nítòótọ́;ìrètí rẹ̀ kì yóò sì gé kúrò.

19. Gbọ́, ìwọ ọmọ mi, kí o sì gbọ́n,kí o sì máa tọ́ àyà rẹ sí ọ̀nà títọ́.

20. Má ṣe wà nínú àwọn ọ̀mùtí;àti àwọn wọ̀bìà alájẹkì ọ̀jẹun;

21. Nítorí pé ọ̀mùtí àti ọ̀jẹun ni yóò di talákà;ìmúni-tòògbé ní sì ń fi àkísà wọ ọkùnrin láṣọ.

22. Fetí sí ti baba rẹ tí ó bí ọ,má sì ṣe gan ìyá rẹ, nígbà tí o bá gbó

23. Ra òtítọ́, kí o má sì ṣe tà á;ra ọgbọ́n pẹ̀lú àti ẹ̀kọ́, àti òye.

24. Baba olódodo ni yóò yọ̀ gidigidi:ẹni tí ó sì bí ọmọ ọlọ́gbọ́n,yóò ní ayọ̀ nínú rẹ̀.

25. Jẹ́ kí bàbá rẹ àti ìyá rẹ ó yọ̀,sì jẹ́ kí inú ẹni tí ó bí ọ dùn.

26. Ọmọ mi, fi àyà rẹ fún mi,kí o sì jẹ́ kí ojú rẹ ní inú-dídùn sí ọ̀nà mi.

Òwe 23