6. Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn ni wọ́n máa ń wí oore wọn jáde,ṣùgbọ́nn kò rọrùn láti rí ènìyàn olóòótọ́.
7. Olódodo ènìyàn a máa gbé ìgbé ayé àìlábùkùìbùkún ni fún àwọn ọmọ rẹ̀ lẹ́yìn rẹ̀.
8. Nígbà tí ọba bá jókóò sórí ilẹ̀ rẹ̀ láti ṣe ìdájọ́yóò fẹ́ gbogbo ibi dànù pẹ̀lú ojú rẹ̀.
9. Táni ó le è wí pé, “Mo ti ṣe ọkàn mi ní mímọ́,mo mọ́, n kò sì lẹ́ṣẹ̀”?
10. Ìdíwọ̀n èké àti òṣùwọ̀n ìrẹ́jẹ Olúwa kórìíra méjèèjì.
11. Kódà a mọ ọmọdé nípa iṣẹ́ rẹ̀nípa pe bóyá iṣẹ́ rẹ mọ́ tàbí pé ó tọ̀nà.
12. Etí tí ó ń gbọ́ àti ojú tí ó ń ríran Olúwa ni ó dá méjèèjì.
13. Má ṣe fẹ́ràn oorun, àìṣe bẹ́ẹ̀ ìwọ yóò di talákàmá ṣe sùn ìwọ yóò sì ní oúnjẹ láti tún fi tọrọ.