Oníwàásù 7:1-7 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Orúkọ rere ṣàn ju ìpara olóòórùn dídùn lọọjọ́ ikú sì dára ju ọjọ́ tí a bí ènìyàn lọ

2. Ó dára láti lọ sí ilé ọ̀fọ̀ju ibi àṣènítorí pé ikú jẹ́ àyànmọ́ gbogbo ènìyànkí alààyè ní èyí ní ọkàn.

3. Ìbànújẹ́ dára ju ẹ̀rín lọÓ le è mú kí ojú rẹ̀ dàrú, ṣùgbọ́n yóò jẹ́ kí àyà rẹ le

4. Ọkàn ọlọgbọ́n wà ní ilé ọ̀fọ̀,ṣùgbọ́n ọkàn òmùgọ̀ ní ilé àríyá.

5. Ó dára láti gba ìbáwí ọlọ́gbọ́n,ju fífetísílẹ̀ sí orin òmùgọ̀ lọ.

6. Gẹ́gẹ́ bí ẹ̀gún ti ń dún lábẹ́ ìkòkòni ẹ̀rín òmùgọ̀,Aṣán sì ni eléyìí pẹ̀lú.

7. Ìrẹ́jẹ a máa ṣọ ọlọ́gbọ́n di òmùgọ̀,àbẹ̀tẹ́lẹ̀ sì máa ń ba ìwà jẹ́ ni.

Oníwàásù 7