Oníwàásù 6:4-8 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

4. Ó wà láìní ìtumọ̀, ó lọ nínú òkùnkùn, nínú òkùnkùn sì ni orúkọ rẹ̀ farapamọ́ sí.

5. Bí ó ti jẹ́ wí pé kò rí oòrùn tàbí mọ ohunkóhun, ó ní ọ̀pọ̀ ìṣinmi ju ti okùnrin náà lọ.

6. Kó dà, bí ó wà láàyè fún ẹgbẹ̀rún ọdún méjì yípo ṣùgbọ́n tí ó kùnà láti gbádùn ohun-ìní rẹ̀. Kìí ṣe ibìkan ni gbogbo wọn ń lọ?

7. Gbogbo wàhálà tí ènìyàn ń ṣe nítorí àtijẹ niṣíbẹ̀ ikùn rẹ̀ kò yó rí

8. Kí ni àǹfàní tí ọlọgbọ́n ènìyàn nílórí aṣiwèrè?Kí ni èrè talákà ènìyànnípa mímọ bí yóò ṣe hùwà níwájú àwọn tó kù?

Oníwàásù 6