Oníwàásù 5:10-14 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

10. Ẹni tí ó bá ní ìfẹ́ owó kì í ní owó ànító,ẹni tí ó bá ní ìfẹ́ sí ọrọ̀ kì í ní ìtẹ́lọ́rùnpẹ̀lú èrè tí ó ń wọlé fún-un.

11. Bí ẹrù bá ti ń pọ̀ síináà ni àwọn tí ó ń jẹ ẹ́ yóò máa pọ̀ síiÈrè e kí ni wọ́n sì jẹ́ sí oní nǹkanbí kò se pé, kí ó máa mú inú ara rẹ dùn nípa rírí wọn?

12. Oorun alágbàṣe a máa dùn,yálà ó jẹun kékeré ni tàbí ó jẹun púpọ̀,ṣùgbọ́n ọ̀pọ̀ ọ̀rọ̀ ọlọ́rọ̀kì í jẹ́ kí ó ṣùn rárá.

13. Mo ti rí ohun tí ó burú gidigidi lábẹ́ oòrùnọrọ̀ tí a kó pamọ́ fún ìparun oní nǹkan.

14. Tàbí ọrọ̀ tí ó ṣọnù nípa àìrí ojúrere,nítorí wí pé bí ó bá ní ọmọkùnrinkò sí ohun tí yóò fi sílẹ̀ fún-un.

Oníwàásù 5