7. Sámúsónì sọ fún un pé, “Nítorí pé ẹ̀yin ṣe èyí, èmi kò dẹṣẹ̀ (dúró) títí èmi yóò fi gbẹ̀ṣan mi lára yín.”
8. Ó kọ lù wọ́n pẹ̀lú ìbínú àti agbára ńlá, ó sì pa ọ̀pọ̀lọpọ̀ nínú wọn. Lẹ́yìn náà ni ó lọ, ó sì dúró nínú ihò àpáta kan nínú àpáta Étamù.
9. Àwọn ará Fílístínì sì dìde ogun sí Júdà, wọ́n ti tan ara wọn ká sí agbégbé Léhì.
10. Àwọn ọkùnrin Júdà sì bèèrè pé, “Èéṣe tí ẹ fi wá gbógun tì wá?”Ìdáhùn wọn ni pé, “Awá láti mú Sámúsónì ní ìgbékùn, kí a ṣe sí i bí òun ti ṣe sí wa.”