15. Àwọn ọmọ Ísírẹ́lì sì dá Olúwa lóhùn pé, “Àwá ti ṣẹ̀, ṣe ohun tí ó bá fẹ́ pẹ̀lú wa, ṣùgbọ́n, jọ̀wọ́ gbà wá sílẹ̀ ná ní àsìkò yìí.”
16. Nígbà náà ni wọ́n kó gbogbo ọlọ́run àjèjì tí ó wà láàárin wọn kúrò wọ́n sì sin Olúwa nìkan, ọkàn rẹ̀ kò sì le gbàgbé ìrora Ísírẹ́lì mọ́.
17. Nígbà tí àwọn ará Ámónì kógun jọ ní Gílíádì láti bá Ísírẹ́lì jà, àwọn ọmọ Ísírẹ́lì gbárajọpọ̀ wọ́n sì tẹ̀dó ogun ní Mísípà.