Nọ́ḿbà 32:39-42 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

39. Àwọn ọmọ Mákírì ọmọ Mánásè lọ sí Gílíádì, wọ́n sì lé àwọn ọmọ Ámórì tí ó wà níbẹ̀.

40. Mósè sì fi àwọn ọmọ Gílíádì fún àwọn ọmọ Mákírì àwọn ìrán Mánásè, wọ́n sì tẹ̀dó ṣíbẹ̀.

41. Jáírì, ọmọ Mánásè gba ibùjókòó wọn, ó sì pè wọ́n ní Háfótù Jáírì.

42. Nébà gbà Kénátì àti àwọn ìtẹ̀dó rẹ̀, ó sì pè é ní Nóbà lẹ́yìn orúkọ ara rẹ̀.

Nọ́ḿbà 32