Nọ́ḿbà 18:25-29 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

25. Olúwa sọ fún Mósè pé,

26. “Sọ fún àwọn ọmọ Léfì kí o sì wí fún wọn pé: ‘Nígbà tí ìdámẹ́wàá bá ń wọlé láti ọ̀dọ̀ àwọn ọmọ Ísírẹ́lì gẹ́gẹ́ bí ogún rẹ. O gbọdọ̀ mú ìdámẹ́wàá lára rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọrẹ Olúwa.

27. A ó ka ọrẹ rẹ gẹ́gẹ́ bí ọkà irúgbìn láti ilé ìpakà tàbí wáìnì láti fún wa.

28. Báyìí ni ìwọ gan an náà yóò mú ọrẹ wa fún Olúwa láti ara ìdámẹ́wàá tí ìwọ gbà láti ọ̀dọ̀ àwọn ọmọ Ísírẹ́lì. Láti ara ìdámẹ́wá ó gbọdọ̀ mú ọrẹ Olúwa fún Árónì àlùfáà.

29. Ìwọ gbọdọ̀ mú wá gẹ́gẹ́ bí ìpín Olúwa èyí tí ó dára jùlọ àti tí ó jẹ́ mímọ́ jùlọ lára gbogbo nǹkan tí wọ́n mú wá fún ọ.’

Nọ́ḿbà 18