Nọ́ḿbà 13:21-24 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

21. Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n gòkè lọ láti yẹ ilẹ̀ náà wò, wọ́n lọ láti Aginjù Ṣínì títí dé Réhóbù lọ́nà Lébò Hámátì.

22. Wọ́n gba Gúsù lọ sí Hébírónì níbi tí Áhímánì, Ṣésáì àti Tálímà tí í se irú ọmọ Ánákì ń gbé. (A ti kọ́ Hébúrónì ní ọdun méje ṣáájú Ṣánì ní Éjíbítì.)

23. Nígbà tí wọ́n dé àfonífojì Éṣíkólù, wọ́n gé ẹ̀ka kan tó ní ìdì èṣo àjàrà gíréèpù kan. Àwọn méjì sì fi ọ̀pá kan gbé e; wọ́n tún mú èṣo pomegíránétì àti èṣo ọ̀pọ̀tọ́ pẹ̀lú.

24. Wọ́n sì sọ ibẹ̀ ní àfonífojì Ésíkólù nítorí ìdí èso gíréépù tí wọ́n gé níbẹ̀.

Nọ́ḿbà 13