Nọ́ḿbà 1:3-17 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

3. Ìwọ àti Árónì ni kí ẹ kà gbogbo ọmọkùnrin Ísírẹ́lì gẹ́gẹ́ bí ìpín wọn láti ọmọ ogún ọdún sókè, àwọn tí ó tó lọ sójú ogun.

4. Kí ẹ mú ọkùnrin kọ̀ọ̀kan tí ó jẹ́ olórí ìdílé rẹ̀ láti ràn yín lọ́wọ́.

5. Orúkọ àwọn ọkùnrin tí yóò ràn ọ́ lọ́wọ́ nìyí:Láti ọ̀dọ̀ Rúbẹ́nì, Élísúrì ọmọ Ṣédéúrì;

6. Láti ọ̀dọ̀ Símónì, Ṣélúmíélì ọmọ Ṣúrísáddáì;

7. Láti ọ̀dọ̀ Júdà, Násónì ọmọ Ámínádàbù;

8. Láti ọ̀dọ̀ Íssákárì, Nítaníẹ́lì ọmọ Ṣúárì;

9. Láti ọ̀dọ̀ Ṣébúlúnì, Élíábù ọmọ Hélónì;

10. Láti ọ̀dọ̀ àwọn sọmọ Jósẹ́fù:láti ọ̀dọ̀ Éfraimù, Elisámà ọmọ Ámíhúdì;Láti ọ̀dọ̀ Mánásè, Gámáélì ọmọ Pedasúrù;

11. Láti ọ̀dọ̀ Bẹ́ńjámínì, Ábídánì ọmọ Gídíónì;

12. Láti ọ̀dọ̀ Dánì, Áhíésérì ọmọ Ámísádáì;

13. Láti ọ̀dọ̀ Áṣérì, Págíélì ọmọ Ókíránì;

14. Láti ọ̀dọ̀ Gáádì, Élíásàfu ọmọ Déúélì;

15. Láti ọ̀dọ̀ Náfítalì, Áhírà ọmọ Énánì.”

16. Àwọn wọ̀nyìí ni wọ́n yàn nínú àwùjọ ènìyàn, olórí àwọn ẹ̀yà baba wọn. Àwọn ni olórí àwọn ẹbí Ísírẹ́lì.

17. Mósè àti Árónì mú àwọn ènìyàn tí a dárúkọ wọ̀nyí

Nọ́ḿbà 1