Nehemáyà 9:36-38 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

36. “Ṣùgbọ́n wò ó, àwa jẹ́ lónìí, àwa jẹ́ ẹrú ní ilẹ̀ tí ìwọ fún àwọn baba ńlá wa, nítorí kí wọn bá máa jẹ èṣo rẹ̀ àti ire mìíràn tí ó mú jáde.

37. Nítorí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ wa, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìkórèe rẹ lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn ọba tí ó fi ṣe olórí wa. Wọ́n ń ṣe àkóso lóríi wa àti lórí ẹran wa bí ó ti wù wọ́n, àwa sì wà nínú ìpónjú ńlá.

38. “Nítorí gbogbo èyí, a ń ṣe àdéhùn tí ó fẹṣẹ̀múlẹ̀, a sì kọ ọ́ sínú ìwé, àwọn olórí ọmọ Léfì àwọn àlùfáà wọn wa sì fi èdìdì wọn dìí.”

Nehemáyà 9