30. Lẹ́yìn rẹ̀ ni, Hananáyà ọmọ Ṣelemáyà, àti Hánúnì ọmọ ẹ̀kẹfà Ṣáláfì, tún apá ibòmíràn ṣe. Lẹ́yìn wọn ni, Mésúlámù ọmọ Berekáyà tún ọ̀kánkán ibùgbé e rẹ̀ ṣe.
31. Lẹ́yìn in rẹ̀ ni, Mákíjà, ọ̀kan nínú àwọn alágbẹ̀dẹ wúrà ṣe àtúnṣe títí dé ilé àwọn ìránṣẹ́ tẹ́ḿpìlì àti àwọn oníṣòwò, ní ọ̀kánkán ibodè àyẹ̀wò títí dé yàrá òkè kọ̀rọ̀;
32. àti láàárin yàrá òkè kọ̀rọ̀ àti ibodè àgùntàn ni àwọn alágbẹ̀dẹ wúrà àti àwọn oníṣòwò tún ṣe.