Nehemáyà 12:17-23 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

17. ti ìdílé Ábíjà, Ṣíkírì;ti ìdílé Míníámínì àti ti ìdílé Móádíà, Pílítaì;

18. ti ìdílé Bílígà, Ṣámúyà;ti ìdílé Ṣémáyà, Jéhónátanì;

19. ti ìdílé Jóíáríbù, Máténáyì;ti ìdílé Jédáíáyà, Húsì;

20. ti ìdílé Ṣálù, Káláyì;ti ìdílé Ámókì, Ébérì;

21. ti ìdílé Hílíkíáyà, Háṣábíáyà;ti ìdílé Jédáíáyà, Nétanẹ́lì.

22. Àwọn olóórí ìdílé àwọn ọmọ Léfì ní ìgbà ayé Élíáṣíbù, Jóíádà, Jóhánánì àti Jádúà, àti pẹ̀lú ti àwọn àlùfáà ni a kọ sílẹ̀ ní ìgbà ìjọba Dáríúsì ará a Páṣíà.

23. Àwọn olórí ìdílé láàrin àwọn ọmọ Léfì títí di àkókò Jóhánánì ọmọ Élíáṣíbù ni a kọ sílẹ̀ nínú ìwé ìtàn.

Nehemáyà 12