Mátíù 26:49-54 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

49. Nísinsìn yìí, Júdásì wá tààrà sọ́dọ̀ Jésù, ó wí pé, “Àlàáfíà, Ráábì” ó fi ẹnu kò ó ní ẹnu.

50. Jésù wí pé, “Ọ̀rẹ́, kí ni nǹkan tí ìwọ bá wá.”Àwọn ìyókù sì sún ṣíwájú wọ́n sì mú Jésù.

51. Sì wò ó, ọ̀kan nínú àwọn tí ó wà pẹ̀lú Jésù na ọwọ́ rẹ̀, ó sì fa idà yọ, ó sì ṣá ọ̀kan tí i ṣe ọmọ-ọ̀dọ̀ olórí àlùfáà, ó sì gé e ní etí sọnù.

52. Jésù wí fún un pé, “Fi idà rẹ bọ àkọ̀ nítorí àwọn tí ó ń fi idà pa ni.

53. Ìwọ kò mọ̀ pé èmi lè béèrè lọ́wọ́ Baba mi kí ó fún mi ju légíónì (6,000) ańgẹ́lì méjìlá? Òun yóò sì fi wọ́n ránṣẹ́ lẹsẹ̀kẹsẹ̀.

54. Ṣùgbọ́n bí mo bá ṣe eléyìí ọ̀nà wo ni a ó fi mú ìwé Mímọ́ ṣẹ, èyí tí ó ti sọ ohun tí ó ṣẹlẹ̀ nísinsìn yìí?”

Mátíù 26