Mátíù 25:27-34 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

27. Nígbà náà ìwọ ìbá kúkú fi owó mi sí ilé ìfowópamọ́ tí èmi bá dé èmi ìbá le gba owó mi pẹ̀lú èrè.

28. “ ‘Ó sì páṣẹ kí a gba tálẹ́ǹtì náà lọ́wọ́ rẹ̀, kí a sì fún ọkùnrin tí ó ní tálẹ́ǹtì mẹ́wàá.

29. Nítorí ẹnikẹ́ni tí ó bá ní a ó fún sí i, yóò sí tún ní sí lọ́pọ̀lọpọ̀. Ṣùgbọ́n láti ọwọ́ ẹni tí kò ní ni a ó ti gbà èyí tí ó ní.

30. Nítorí ìdi èyí, gbé aláìlérè ọmọ-ọ̀dọ̀, jù ú sínú òkùnkùn lóde, ibẹ̀ niẹ̀kún òun ìpayínkeke yóò gbé wà.’

31. “Ṣùgbọ́n nígbà ti Ọmọ-Ènìyàn yóò wá nínú ògo rẹ̀ pẹ̀lú gbogbo àwọn ańgẹ́lì rẹ̀ nígbà náà ni yóò jókòó lórí ìtẹ́ ògo ní ọ̀run.

32. Gbogbo orílẹ̀-èdè ni a ó kó jọ níwájú rẹ̀, òun yóò sì ya àwọn ènìyàn ayé sí ọ̀tọ̀ gẹ́gẹ́ bí olùṣọ́ àgùntàn ṣe é ya àgùntàn kúrò lára àwọn ewúrẹ́.

33. Òun yóò sì fi àgùntàn sí ọwọ́ ọ̀tún àti ewúrẹ́ sí ọwọ́ òsì.

34. “Nígbà náà ni Ọba yóò wí fún àwọn tí ó wà lọ́wọ́ ọ̀tún pé, ‘Ẹ wá, ẹ̀yin tí Baba mi ti bùkún fún, ẹ jogún ìjọba tí a ti pèsè fún yín láti ìpìlẹ̀ṣẹ̀ ayé.

Mátíù 25