Mátíù 22:36-39 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

36. Ó wí pé, “Olùkọ́ èwo ni ó ga jùlọ nínú àwọn òfin?”

37. Jésù dáhùn pé, “ ‘Fẹ́ Olúwa Ọlọ́run rẹ pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ, gbogbo ẹ̀mí rẹ àti gbogbo inú rẹ.’

38. Èyí ni òfin àkọ́kọ́ àti èyí tí ó tóbi jùlọ.

39. Èkejì tí ó tún dàbí rẹ̀ ní pé, ‘Fẹ́ràn ọmọ ẹni kejì rẹ gẹ́gẹ́ bí ara rẹ.’

Mátíù 22