36. Ó wí pé, “Olùkọ́ èwo ni ó ga jùlọ nínú àwọn òfin?”
37. Jésù dáhùn pé, “ ‘Fẹ́ Olúwa Ọlọ́run rẹ pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ, gbogbo ẹ̀mí rẹ àti gbogbo inú rẹ.’
38. Èyí ni òfin àkọ́kọ́ àti èyí tí ó tóbi jùlọ.
39. Èkejì tí ó tún dàbí rẹ̀ ní pé, ‘Fẹ́ràn ọmọ ẹni kejì rẹ gẹ́gẹ́ bí ara rẹ.’