13. Nígbà tí Jésù sì dé Kesaríà-Fílípì, ó bi àwọn ọmọ ẹ̀yin rẹ̀ pé, “Ta ni àwọn ènìyàn ń fi Ọmọ ènìyàn pè?”
14. Wọ́n dá a lóhùn pé, “Àwọn kan ni Jòhánù onítẹ̀bọ́mì ni, àwọn mìíràn wí pé, Èlíjà ni, àwọn mìíràn wí pé, Jeremáyà ni, tàbí ọ̀kan nínú àwọn wòlíì.”
15. “Ṣùgbọ́n ìwọ ń kọ” Ó bi í léèrè pé, “Ta ni ìwọ rò pé mo jẹ́?”
16. Símónì Pétérù dáhùn pé, “Ìwọ ni Kírísítì náà, Ọmọ Ọlọ́run alààyè”